Akonimoogba egbe agbaboolu U-17 ti o gba ife
eye idije agbaye ni orilèdè Chile, iyen Emmanuel Amuneke, ni ajo ti on ri si
oro ere boolu lorilede wa, iyen Nigeria football
federation (NFF), ti fun ni ipo akonimoogba egbe agbaboolu U-20.
Gege bi iroyin ti o ti odo ajo NFF jade, Manu
Garuba ni yio si duro ni ipo re gege bi
akonimoogba U-20 nigba ti Amuneke yio duro ni ipo re gege bi akonimoogba U-17,
ti yio si je igbákeji fun Manu Garuba ni ipele U-20.
Gege bi ohun ti Amaju Pinnick ti o je Aare NFF
so, Manu Garuba ati Amuneke ni o ni ibasepo ti o dara laarin ara won eyi ti yio
ran ere boolu lowo lorilede yii.
Bi a ko ba gbagbe, ogbeni Amuneke ni igbákeji
Manu Garuba nigba ti egbe agbaboolu U-17 gba ife eye agbaye ni orilèdè United Arab Emirates(UAE) ni odun 2013.
No comments:
Post a Comment